1. Ẹ wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah al-Baƙọrah; 2:15.
1. Nínú āyah yìí, wọ́n pe “àdúà” ní “ẹ̀sìn”. Ó tún jẹyọ bẹ́ẹ̀ nínú sūrah Gāfir; 40:60. Èyí ti fi hàn kedere pé, ẹ̀sìn ni àdúà ṣíṣe. Nítorí náà, bí ẹlẹ́sìn tí kì í ṣe ẹlẹ́sìn ’Islām bá pe mùsùlùmí kan lọ síbi àdúà lórí ìlànà ẹ̀sìn kèfèrí, yálà ìlànà abọ̀rìṣà tàbí ìlànà nasọ̄rọ̄, ó ń dá ète láti pe mùsùlùmí yẹn lọ sínú ẹ̀sìn kèfèrí rẹ̀ ni. Bí mùsùlùmí yẹn bá jẹ́pè kèfèrí náà, òun náà ti di kèfèrí nìyẹn.