1. Èyí fi rinlẹ̀ pé, Allāhu - Ọba tí kò ní àfiwé àti àfijọ nínú àwọn ẹ̀dá Rẹ̀ - ní ọwọ́ ní ti pàápàá àti ní ti bí ó ṣe bá títóbi Rẹ̀ mu.
1. “Ẹni tí Allāhu bá fẹ́” fún àforíjìn Rẹ̀, ó máa lè tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Allāhu. “Ẹni tí Allāhu bá fẹ́ jẹ níyà” kò níí lè tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Allāhu, kò sì níí ronú pìwàdà.
1. Ẹ wo bí àwọn olùsásẹ́yìn, àwọn munāfiki ṣe ń fi ẹ̀sùn burúkú kan Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - àti àwọn onígbàgbọ́ òdodo. Wọ́n ní wọ́n ń ṣe kèéta àwọn ni! Ṣé ó sì rọrùn fún Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a - láti ṣe kèéta àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀, ẹni tí Allāhu fi ìwà tó ga jùlọ ròyìn? Ìbẹ̀rẹ̀ orí burúkú ni fún ẹ̀dá kan nígbà náà láti fi ẹ̀sùn kan Ànábì - kí ìkẹ́ àti ọlà Allāhu máa bá a -.