1. Àpẹ̀ẹrẹ àwọn olùṣìnà jùlọ yìí ni àwọn nasọ̄rọ̄ tí wọ́n ń pe Ànábì ‘Īsā ọmọ Mọryam - kí ọlà Allāhu máa bá a - pẹ̀lú àwáwí pé ó wà láàyè nínú sánmọ̀, àmọ́ tí wọn kò mọ̀ pé ó kàn wà nínú sánmọ̀ ni, kò lè gbọ́ ìpè wọn áḿbọ̀sìbọ́sí pé ó máa jẹ́pè wọn. Allāhu nìkan ṣoṣo l’Ó lè jẹ́pè àwọn ẹrúsìn rẹ̀, onígbàgbọ́ òdodo.