1. Ìyẹn ni pé, kí Allāhu má ṣe fi ọ̀tá ẹ̀sìn wa borí wa. Tàbí àdánwò tó máa kàn wá tí àwọn ọ̀tá ẹ̀sìn wa yóò fi lérò pé a kì í ṣe ẹni Allāhu, kí Allāhu má ṣe fi kàn wá.
1. Ìyẹn nígbà tí ẹ̀rù ń bà wọ́n láti máa lọ kírun nínú mọ́sálásí nítorí iṣẹ́ aburú ọwọ́ Fir'aon àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
1. “torí kí wọ́n lè ṣẹ́rí àwọn ènìyàn kúrò lójú ọ̀nà (ẹ̀sìn) Rẹ” ìyẹn ni pé, Allāhu fi oore ayé ṣe ẹ̀dẹ fún wọn.