1. Wo ìtọsẹ̀-ọ̀rọ̀ sūrah āli-‘Imrọ̄n; 3:7.
1. Ìtúmọ̀ mìíràn fún āyah yìí, “Ó súnmọ́ pé (ẹ̀yin aláìsàn ọkàn wọ̀nyí) bí ẹ bá dé orí ipò àṣẹ, ẹ óò máa ṣèbàjẹ́ lórí ilẹ̀ àti pé ẹ óò máa já okùn-ìbí yín?”
1. Ìyẹn ni pé, àwọn aláìsàn ọkàn nínú àwọn mùsùlùmí, ìyẹn àwọn tí wọn ń sá fún ogun ẹ̀sìn, wọ́n lọ bá àwọn yẹhudi, ìyẹn àwọn tí wọ́n kírira pé Ànábì ìkẹ́yìn dìde láààrin àwọn ọmọ Ànábì ’Ismā‘īl. Igun alágàbàǹgebè sì ń sàdéhùn àtìlẹ́yìn fún igun yẹhudi.