1. Ọmọ ‘Abbās - kí Allāhu yọ́nú sí àwọn méjèèjì - “Kódà kí ó jẹ́ ìbálòpọ̀ ẹ̀ẹ̀ kan péré.” 2. Gbólóhùn yìí jẹmọ́ sūrah al-Baƙọrah; 2:236 - 237 nítorí pé, ọ̀rọ̀ obìnrin tí ọkọ fẹ́ tán tí ìkọ̀sílẹ̀ wáyé láààrin wọn ṣíwájú ìbálòpọ̀, èyí ló jẹyọ nínú āyah méjèèjì yẹn. Àmọ́ nínú āyah yìí ìkọ̀sílẹ̀ wáyé lẹ́yìn ìbálòpọ̀ díẹ̀, ó kéré parí ẹ̀ẹ̀ kan péré. Ó gbọ́dọ̀ san sọ̀daàkí rẹ̀ fún un. 3. Ìyẹn ni pé, kò sí aburú tí obìnrin náà bá gba àdínkù, kò sì sí aburú tí ọkọ bá fún un ní àlékún sí òdíwọ̀n sọ̀daàkí tí wọ́n dìjọ fẹnukò sí.
1. Musāfihah ni onísìná obìnrin tí kò sí lábẹ́ ọkọ. Muttẹkithatu- ’akdān ni onísìná obìnrin tí ó wà lábẹ́ ọkọ. 2. Ìyẹn ni pé, ẹrúbìnrin, tí ó bá ṣe sìná, kòbókò àádọ́ta ni ìjìyà rẹ̀, kì í ṣe lílẹ̀-lókò-pa nítorí pé, lílẹ̀-lókò-pa kò ṣe é pín sí méjì.